Ojúewé ìbẹ̀rẹ̀ › Àwọn Súrà › Súrà Al-Mutaffifin
Súrà Al-Mutaffifin المطففين
36 verses · Mecca · revelation order 86
بِسْمِ ٱللَّهِ ٱلرَّحْمَٰنِ ٱلرَّحِيمِ وَيْلٌ لِّلْمُطَفِّفِينَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ègbé ni fún àwọn olùdín-òṣùwọ̀n-kù,
See all translations of this verse →
ٱلَّذِينَ إِذَا ٱكْتَالُوا۟ عَلَى ٱلنَّاسِ يَسْتَوْفُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael àwọn (òǹtajà) tó jẹ́ pé nígbà tí wọ́n bá wọn n̄ǹkan lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn,[1] wọ́n á gbà á ní ẹ̀kún,
See all translations of this verse →
وَإِذَا كَالُوهُمْ أَو وَّزَنُوهُمْ يُخْسِرُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael nígbà tí àwọn (òǹtajà náà) bá sì lo ìwọ̀n fún àwọn (òǹrajà) tàbí lo òṣùwọ̀n fún wọn, wọn yóò dín in kù.
See all translations of this verse →
أَلَا يَظُنُّ أُو۟لَٰٓئِكَ أَنَّهُم مَّبْعُوثُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ṣé àwọn wọ̀nyẹn kò mọ̀ dájú pé dájúdájú A máa gbé wọn dìde
See all translations of this verse →
لِيَوْمٍ عَظِيمٍ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael ní Ọjọ́ ńlá kan?
See all translations of this verse →
يَوْمَ يَقُومُ ٱلنَّاسُ لِرَبِّ ٱلْعَٰلَمِينَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ní ọjọ́ tí àwọn ènìyàn yóò dìde dúró fún Olúwa gbogbo ẹ̀dá.
See all translations of this verse →
كَلَّآ إِنَّ كِتَٰبَ ٱلْفُجَّارِ لَفِى سِجِّينٍ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ní ti òdodo dájúdájú ìwé iṣẹ́ àwọn ẹni burúkú (tó ń dín òṣùwọ̀n kù) kúkú máa wà nínú Sijjīn.
See all translations of this verse →
وَمَآ أَدْرَىٰكَ مَا سِجِّينٌ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ Sijjīn!
See all translations of this verse →
كِتَٰبٌ مَّرْقُومٌ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ìwé tí wọ́n ti kọ iṣẹ́ aburú ẹ̀dá sínú rẹ̀ (tí wọ́n sì fi pamọ́ sínú ilẹ̀ keje ni Sijjīn).
See all translations of this verse →
وَيْلٌ يَوْمَئِذٍ لِّلْمُكَذِّبِينَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ní ọjọ́ yẹn, ègbé ni fún àwọn olùpe-òdodo- nírọ́,
See all translations of this verse →
ٱلَّذِينَ يُكَذِّبُونَ بِيَوْمِ ٱلدِّينِ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael àwọn tó ń pe Ọjọ́ ẹ̀san ní irọ́.
See all translations of this verse →
وَمَا يُكَذِّبُ بِهِۦٓ إِلَّا كُلُّ مُعْتَدٍ أَثِيمٍ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Kò sì sí ẹni tó ń pè é ní irọ́ àyàfi gbogbo alákọyọ, ẹlẹ́ṣẹ̀.
See all translations of this verse →
إِذَا تُتْلَىٰ عَلَيْهِ ءَايَٰتُنَا قَالَ أَسَٰطِيرُ ٱلْأَوَّلِينَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Nígbà tí wọ́n bá ń ké àwọn āyah Wa fún un, ó máa wí pé: “Àwọn àkọsílẹ̀ àlọ́ àwọn ẹni àkọ́kọ́ (nìwọ̀nyí).”
See all translations of this verse →
كَلَّا بَلْ رَانَ عَلَىٰ قُلُوبِهِم مَّا كَانُوا۟ يَكْسِبُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Rárá (al-Ƙur’ān kì í ṣe àkọsílẹ̀ àlọ́ àwọn ẹni àkọ́kọ́) bí kò ṣe pé ohun tí wọ́n ń ṣe níṣẹ́ aburú l’ó jọba lórí ọkàn wọn.
See all translations of this verse →
كَلَّآ إِنَّهُمْ عَن رَّبِّهِمْ يَوْمَئِذٍ لَّمَحْجُوبُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Rárá (kò rí bí wọ́n ṣe rò ó sí sẹ́), dájúdájú wọn yóò wà nínú gàgá, wọn kò sì níí rí Olúwa wọn ní ọjọ́ yẹn.
See all translations of this verse →
ثُمَّ إِنَّهُمْ لَصَالُوا۟ ٱلْجَحِيمِ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Lẹ́yìn náà, dájúdájú wọn yóò wọ inú iná Jẹhīm.
See all translations of this verse →
ثُمَّ يُقَالُ هَٰذَا ٱلَّذِى كُنتُم بِهِۦ تُكَذِّبُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Lẹ́yìn náà, wọ́n máa sọ (fún wọn) pe: “Èyí ni ohun tí ẹ̀ ń pè ní irọ́.”
See all translations of this verse →
كَلَّآ إِنَّ كِتَٰبَ ٱلْأَبْرَارِ لَفِى عِلِّيِّينَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ní ti òdodo, dájúdájú ìwé iṣẹ́ àwọn ẹni rere wà nínú ‘illiyyūn.
See all translations of this verse →
وَمَآ أَدْرَىٰكَ مَا عِلِّيُّونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Kí sì l’ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ ‘illiyyūn!
See all translations of this verse →
كِتَٰبٌ مَّرْقُومٌ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ìwé tí wọ́n ti kọ iṣẹ́ rere ẹ̀dá sínú rẹ̀ (tí wọ́n sì fi pamọ́ sí òkè sánmọ̀ ni ‘illiyyūn).
See all translations of this verse →
يَشْهَدُهُ ٱلْمُقَرَّبُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Àwọn (mọlāika) tí wọ́n súnmọ́ Allāhu ń jẹ́rìí sí i.
See all translations of this verse →
إِنَّ ٱلْأَبْرَارَ لَفِى نَعِيمٍ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Dájúdájú àwọn ẹni rere máa wà nínú ìgbádùn.
See all translations of this verse →
عَلَى ٱلْأَرَآئِكِ يَنظُرُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Wọn yóò máa wòran lórí àwọn ibùsùn.
See all translations of this verse →
تَعْرِفُ فِى وُجُوهِهِمْ نَضْرَةَ ٱلنَّعِيمِ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ìwọ yóò dá ìtutù ojú ìgbádùn mọ̀ nínú ojú wọn.
See all translations of this verse →
يُسْقَوْنَ مِن رَّحِيقٍ مَّخْتُومٍ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Wọn yóò máa fún wọn mu nínú ọtí onídèérí.
See all translations of this verse →
خِتَٰمُهُۥ مِسْكٌ وَفِى ذَٰلِكَ فَلْيَتَنَافَسِ ٱلْمُتَنَٰفِسُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Àlùmísìkí ni (òórùn) ìparí rẹ̀. Kí àwọn alápàáǹtètè ṣàpáǹtètè nínú ìyẹn.
See all translations of this verse →
وَمِزَاجُهُۥ مِن تَسْنِيمٍ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Tẹsnīm ni wọ́n yóò máa pòpọ̀ (mọ́ ọtí náà).
See all translations of this verse →
عَيْنًا يَشْرَبُ بِهَا ٱلْمُقَرَّبُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael (Tẹsnīm ni) omi ìṣẹ́lẹ̀rú kan, tí àwọn olùsúnmọ́ (Allāhu) yóò máa mu.
See all translations of this verse →
إِنَّ ٱلَّذِينَ أَجْرَمُوا۟ كَانُوا۟ مِنَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُوا۟ يَضْحَكُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Dájúdájú àwọn tó dẹ́ṣẹ̀, wọ́n máa ń fi àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo rẹ́rìn-ín.
See all translations of this verse →
وَإِذَا مَرُّوا۟ بِهِمْ يَتَغَامَزُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Nígbà tí wọ́n bá gba ẹ̀gbẹ́ wọn kọjá, (àwọn olùdẹ́ṣẹ̀) yóò máa ṣẹ́jú síra wọn ní ti yẹ̀yẹ́.
See all translations of this verse →
وَإِذَا ٱنقَلَبُوٓا۟ إِلَىٰٓ أَهْلِهِمُ ٱنقَلَبُوا۟ فَكِهِينَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Nígbà tí wọ́n bá sì padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wọn, wọ́n á padà tí wọn yóò máa ṣe fáàrí.
See all translations of this verse →
وَإِذَا رَأَوْهُمْ قَالُوٓا۟ إِنَّ هَٰٓؤُلَآءِ لَضَآلُّونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Àti pé nígbà tí wọ́n bá rí (àwọn onígbàgbọ́ òdodo) wọ́n á wí pé: “Dájúdájú àwọn wọ̀nyí ni olùṣìnà.”
See all translations of this verse →
وَمَآ أُرْسِلُوا۟ عَلَيْهِمْ حَٰفِظِينَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Àwa kò sì rán wọn ní iṣẹ́ olùṣọ́ sí wọn.
See all translations of this verse →
فَٱلْيَوْمَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُوا۟ مِنَ ٱلْكُفَّارِ يَضْحَكُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Nítorí náà, ní òní àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo yóò fi àwọn aláìgbàgbọ́ rẹ́rìn-ín.
See all translations of this verse →
عَلَى ٱلْأَرَآئِكِ يَنظُرُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Wọn yóò máa wòran lórí àwọn ibùsùn.
See all translations of this verse →
هَلْ ثُوِّبَ ٱلْكُفَّارُ مَا كَانُوا۟ يَفْعَلُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael Ṣebí wọ́n ti fi ohun tí àwọn aláìgbàgbọ́ ń ṣe níṣẹ́ san wọ́n lẹ́san (báyìí)?
See all translations of this verse →
← Súrà Al-Infitaar
Súrà Al-Inshiqaaq →
Looking for a topic? Try the meaning search — your question is scanned across all 6,236 verses.
→
Arabic text and translations via Tanzil and QuranEnc — verbatim, unmodified · Translations belong to their translators and are not the Qur'an itself
This is a research aid, not a source of religious rulings.