Súrà An-Naba النبإ
40 verses · Mecca · revelation order 80
بِسْمِ ٱللَّهِ ٱلرَّحْمَٰنِ ٱلرَّحِيمِ عَمَّ يَتَسَآءَلُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNípa kí ni wọ́n ń bíra wọn léèrè ná?
See all translations of this verse →
عَنِ ٱلنَّبَإِ ٱلْعَظِيمِ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNípa ìró ìkọ̀kọ̀ ńlá ni,
See all translations of this verse →
ٱلَّذِى هُمْ فِيهِ مُخْتَلِفُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelèyí tí wọ́n ń yapa-ẹnu lórí rẹ̀.
See all translations of this verse →
كَلَّا سَيَعْلَمُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelRárá! Wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
See all translations of this verse →
ثُمَّ كَلَّا سَيَعْلَمُونَ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelLẹ́yìn náà, rárá sẹ́, wọ́n ń bọ̀ wá mọ̀.
See all translations of this verse →
أَلَمْ نَجْعَلِ ٱلْأَرْضَ مِهَٰدًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelǸjẹ́ Àwa kò ṣe ilẹ̀ ní ìtẹ́ bí,
See all translations of this verse →
وَٱلْجِبَالَ أَوْتَادًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti àwọn àpáta ní èèkàn (fún ilẹ̀)?
See all translations of this verse →
وَخَلَقْنَٰكُمْ أَزْوَٰجًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelA sì ṣẹ̀dá yín ní oríṣiríṣi (akọ àti abo).
See all translations of this verse →
وَجَعَلْنَا نَوْمَكُمْ سُبَاتًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelA ṣe oorun yín ní ìsinmi.
See all translations of this verse →
وَجَعَلْنَا ٱلَّيْلَ لِبَاسًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelA tún ṣe alẹ́ ní ìbora.
See all translations of this verse →
وَجَعَلْنَا ٱلنَّهَارَ مَعَاشًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelA tún ṣe ọ̀sán ní (àsìkò fún) wíwá ìjẹ-ìmu.
See all translations of this verse →
وَبَنَيْنَا فَوْقَكُمْ سَبْعًا شِدَادًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelA tún mọ sánmọ̀ méje tó lágbára sókè yín.
See all translations of this verse →
وَجَعَلْنَا سِرَاجًا وَهَّاجًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelA tún ṣe òòrùn ní ìmọ́lẹ̀ tó ń tàn gbòlà.
See all translations of this verse →
وَأَنزَلْنَا مِنَ ٱلْمُعْصِرَٰتِ مَآءً ثَجَّاجًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÀti pé A sọ omi tó ń bọ́ tẹ̀léra wọn kalẹ̀ láti inú àwọn ẹ̀ṣújò
See all translations of this verse →
لِّنُخْرِجَ بِهِۦ حَبًّا وَنَبَاتًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelnítorí kí Á lè fi mú kóró èso àti irúgbìn jáde
See all translations of this verse →
وَجَنَّٰتٍ أَلْفَافًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelpẹ̀lú àwọn ọgbà tó kún digbí fún n̄ǹkan oko.
See all translations of this verse →
إِنَّ يَوْمَ ٱلْفَصْلِ كَانَ مِيقَٰتًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú ọjọ́ ìpínyà, ó ní gbèdéke àkókò kan.
See all translations of this verse →
يَوْمَ يُنفَخُ فِى ٱلصُّورِ فَتَأْتُونَ أَفْوَاجًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(Ìyẹn ni) ọjọ́ tí wọ́n á fọn fèrè oníwo fún àjíǹde. Ẹ̀yin yó sì máa wá níjọ-níjọ.
See all translations of this verse →
وَفُتِحَتِ ٱلسَّمَآءُ فَكَانَتْ أَبْوَٰبًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelWọ́n sì máa ṣí sánmọ̀ sílẹ̀. Ó sì máa di àwọn ìlẹ̀kùn.
See all translations of this verse →
وَسُيِّرَتِ ٱلْجِبَالُ فَكَانَتْ سَرَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelWọ́n máa mú àwọn àpáta rìn (bọ́ sí àyè mìíràn). Ó sì máa di ahúnpeéná.
See all translations of this verse →
إِنَّ جَهَنَّمَ كَانَتْ مِرْصَادًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú iná Jahanamọ, ó lúgọ sílẹ̀ lójú ọ̀nà.
See all translations of this verse →
لِّلطَّٰغِينَ مَـَٔابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(Ó jẹ́) ibùgbé fún àwọn alákọyọ.
See all translations of this verse →
لَّٰبِثِينَ فِيهَآ أَحْقَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelWọn yóò máa gbé inú rẹ̀ fún ìgbà gbọọrọ.
See all translations of this verse →
لَّا يَذُوقُونَ فِيهَا بَرْدًا وَلَا شَرَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelWọn kò níí rí ìtura tàbí ohun mímu kan tọ́wò nínú rẹ̀,
See all translations of this verse →
إِلَّا حَمِيمًا وَغَسَّاقًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàyàfi omi tó gbóná parí àti àwọnúwẹ̀jẹ̀.
See all translations of this verse →
جَزَآءً وِفَاقًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(Ó jẹ́) ẹ̀san tó ṣe wẹ́kú (iṣẹ́ wọn).
See all translations of this verse →
إِنَّهُمْ كَانُوا۟ لَا يَرْجُونَ حِسَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú wọn kì í retí ìṣírò-iṣẹ́.
See all translations of this verse →
وَكَذَّبُوا۟ بِـَٔايَٰتِنَا كِذَّابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelWọ́n sì pe àwọn āyah Wa ní irọ́ gan-an.
See all translations of this verse →
وَكُلَّ شَىْءٍ أَحْصَيْنَٰهُ كِتَٰبًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelGbogbo n̄ǹkan sì ni A ti ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú Tírà kan.
See all translations of this verse →
فَذُوقُوا۟ فَلَن نَّزِيدَكُمْ إِلَّا عَذَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNítorí náà, ẹ tọ́ (ìyà) wò. A ò sì níí ṣe àlékún kan fún yín bí kò ṣe ìyà.
See all translations of this verse →
إِنَّ لِلْمُتَّقِينَ مَفَازًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú ìgbàlà wà fún àwọn olùbẹ̀rù (Allāhu).
See all translations of this verse →
حَدَآئِقَ وَأَعْنَٰبًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÀwọn ọgbà oko àti èso àjàrà,
See all translations of this verse →
وَكَوَاعِبَ أَتْرَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti àwọn ọlọ́mọge, tí wọn kò júra wọn lọ lọ́jọ́-orí,
See all translations of this verse →
وَكَأْسًا دِهَاقًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti ife ọtí tó kún dẹnu (ni ẹ̀san wọn).
See all translations of this verse →
لَّا يَسْمَعُونَ فِيهَا لَغْوًا وَلَا كِذَّٰبًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelWọn kò níí gbọ́ ìsọkúsọ àti ọ̀rọ̀ irọ́ nínú rẹ̀.
See all translations of this verse →
جَزَآءً مِّن رَّبِّكَ عَطَآءً حِسَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(Ó jẹ́) ẹ̀san láti ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ, (ó sì jẹ́) ọrẹ ní ìbámu sí ìṣírò-iṣẹ́ (wọn).
See all translations of this verse →
رَّبِّ ٱلسَّمَٰوَٰتِ وَٱلْأَرْضِ وَمَا بَيْنَهُمَا ٱلرَّحْمَٰنِ لَا يَمْلِكُونَ مِنْهُ خِطَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(Ẹsan náà wá láti ọ̀dọ̀) Olúwa àwọn sánmọ̀, ilẹ̀ àti ohun tó wà láààrin méjèèjì, Àjọkẹ́-ayé. Wọn kò sì ní ìkápá ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ Rẹ̀.
See all translations of this verse →
يَوْمَ يَقُومُ ٱلرُّوحُ وَٱلْمَلَٰٓئِكَةُ صَفًّا لَّا يَتَكَلَّمُونَ إِلَّا مَنْ أَذِنَ لَهُ ٱلرَّحْمَٰنُ وَقَالَ صَوَابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelỌjọ́ tí mọlāika Jibrīl àti àwọn mọlāika (mìíràn) yóò dúró ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́. Wọn kò sì níí sọ̀rọ̀ àfi ẹni tí Àjọké-ayé bá yọ̀ǹda fún. Onítọ̀ún sì máa sọ̀rọ̀ tó máa ṣe wẹ́kú.
See all translations of this verse →
ذَٰلِكَ ٱلْيَوْمُ ٱلْحَقُّ فَمَن شَآءَ ٱتَّخَذَ إِلَىٰ رَبِّهِۦ مَـَٔابًا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÌyẹn ni ọjọ́ òdodo. Nítorí náà, ẹni tí ó bá fẹ́ kí ó mú ọ̀nà tó máa gbà ṣẹ́rí padà sí ọ̀dọ̀ Olúwa rẹ̀ pọ̀n (ní ti ìronúpìwàdà).
See all translations of this verse →
إِنَّآ أَنذَرْنَٰكُمْ عَذَابًا قَرِيبًا يَوْمَ يَنظُرُ ٱلْمَرْءُ مَا قَدَّمَتْ يَدَاهُ وَيَقُولُ ٱلْكَافِرُ يَٰلَيْتَنِى كُنتُ تُرَٰبًۢا
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú A fi ìyà tó súnmọ́ ṣe ìkìlọ̀ fún yín. Ọjọ́ tí ènìyàn yóò máa wo ohun tí ó tì síwájú, aláìgbàgbọ́ yó sì wí pé: “Yéè, èmi ìbá sì jẹ́ erùpẹ̀, (èmi ìbá là nínú ìyà).”
See all translations of this verse →
Looking for a topic? Try the meaning search — your question is scanned across all 6,236 verses.
→