Súrà Ad-Dhuhaa الضحى
11 verses · Mecca · revelation order 11
بِسْمِ ٱللَّهِ ٱلرَّحْمَٰنِ ٱلرَّحِيمِ وَٱلضُّحَىٰ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelAllāhu fi ìyálẹ̀ta búra.
See all translations of this verse →
وَٱلَّيْلِ إِذَا سَجَىٰ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÓ tún fi alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú búra.
See all translations of this verse →
مَا وَدَّعَكَ رَبُّكَ وَمَا قَلَىٰ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelOlúwa rẹ kò pa ọ́ tì, kò sì bínú sí ọ.
See all translations of this verse →
وَلَلْـَٔاخِرَةُ خَيْرٌ لَّكَ مِنَ ٱلْأُولَىٰ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú ọ̀run lóore fún ọ ju ayé.
See all translations of this verse →
وَلَسَوْفَ يُعْطِيكَ رَبُّكَ فَتَرْضَىٰٓ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú láìpẹ́ Olúwa rẹ máa fún ọ ní (oore púpọ̀ ní ọ̀run). Nítorí náà, o sì máa yọ́nú sí i.
See all translations of this verse →
أَلَمْ يَجِدْكَ يَتِيمًا فَـَٔاوَىٰ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelṢé (Allāhu) kò rí ọ ní ọmọ-òrukàn ni? Ó sì fún ọ ní ibùgbé.
See all translations of this verse →
وَوَجَدَكَ ضَآلًّا فَهَدَىٰ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÓ sì rí ọ ní aláìmọ̀nà (ìyẹn ṣíwájú ìsọ̀kalẹ̀ ìmísí). Ó sì fi ọ̀nà mọ̀ ọ́.[1]
See all translations of this verse →
وَوَجَدَكَ عَآئِلًا فَأَغْنَىٰ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÓ tún rí ọ ní aláìní, Ó sì rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀.
See all translations of this verse →
فَأَمَّا ٱلْيَتِيمَ فَلَا تَقْهَرْ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNítorí náà, ní ti ọmọ-òrukàn, má ṣe jẹ gàba (lé e lórí).
See all translations of this verse →
وَأَمَّا ٱلسَّآئِلَ فَلَا تَنْهَرْ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNí ti alágbe, má sì ṣe jágbe (mọ́ ọn).
See all translations of this verse →
وَأَمَّا بِنِعْمَةِ رَبِّكَ فَحَدِّثْ
Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNí ti ìdẹ̀ra Olúwa rẹ, sọ ọ́ jáde.
See all translations of this verse →
Looking for a topic? Try the meaning search — your question is scanned across all 6,236 verses.
→