caseriqÌwádìí ìtumọ̀ nínú Al-Ƙur'ān

Súrà At-Takwir التكوير

29 verses · Mecca · revelation order 7

بِسْمِ ٱللَّهِ ٱلرَّحْمَٰنِ ٱلرَّحِيمِ إِذَا ٱلشَّمْسُ كُوِّرَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNígbà tí wọ́n bá ká òòrùn kóróbójó dànù,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلنُّجُومُ ٱنكَدَرَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí àwọn ìràwọ̀ bá já bọ́ káàkiri,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلْجِبَالُ سُيِّرَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá mú àwọn àpáta rìn (kúrò ní àyè wọn, tí wọ́n kù wọ́n dànù),

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلْعِشَارُ عُطِّلَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá pa àwọn ràkúnmí aboyún tì,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلْوُحُوشُ حُشِرَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá ko àwọn ẹranko jọ,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلْبِحَارُ سُجِّرَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá mú àwọn agbami odò gbiná,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلنُّفُوسُ زُوِّجَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá so àwọn ẹ̀mí pọ̀ mọ́ra wọn, (ẹni rere pẹ̀lú ẹni rere, ẹni ibi pẹ̀lú ẹni ibi)

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلْمَوْءُۥدَةُ سُئِلَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí ọmọbìnrin tí wọ́n bò mọ́lẹ̀ láàyè bá bèèrè pé

See all translations of this verse →

بِأَىِّ ذَنۢبٍ قُتِلَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelẹ̀ṣẹ̀ wo ni wọ́n pa òun fún,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلصُّحُفُ نُشِرَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá ṣí àwọn tákàdá (iṣẹ́ ẹ̀dá) sílẹ̀,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلسَّمَآءُ كُشِطَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá ká sánmọ̀ kúrò lókè,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلْجَحِيمُ سُعِّرَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá mú iná Jẹhīm jò fòfò,

See all translations of this verse →

وَإِذَا ٱلْجَنَّةُ أُزْلِفَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelàti nígbà tí wọ́n bá sún Ọgbà Ìdẹ̀ra mọ́ (àwọn onígbàgbọ́ òdodo),

See all translations of this verse →

عَلِمَتْ نَفْسٌ مَّآ أَحْضَرَتْ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(nígbà náà ni) ẹ̀mí (kọ̀ọ̀kan) yóò mọ ohun tí ó mú wá (nínú iṣẹ́ ire àti iṣẹ́ ibi).

See all translations of this verse →

فَلَآ أُقْسِمُ بِٱلْخُنَّسِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNítorí náà, Èmi (Allāhu) ń fi àwọn ìràwọ̀ tó ń yọ ní alẹ́, tó ń wọ̀ọ̀kùn ní ọ̀sán búra,

See all translations of this verse →

ٱلْجَوَارِ ٱلْكُنَّسِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(ìyẹn) àwọn ìràwọ̀ tó ń rìn lọ rìn bọ̀, tó ń wọ̀ọ̀kùn sí ibùwọ̀ wọn.

See all translations of this verse →

وَٱلَّيْلِ إِذَا عَسْعَسَ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelMo tún fi alẹ́ nígbà tí ó bá lọ búra.[1]

See all translations of this verse →

وَٱلصُّبْحِ إِذَا تَنَفَّسَ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelMo tún fi òwúrọ̀ nígbà tí ó bá mọ́lẹ̀ búra.

See all translations of this verse →

إِنَّهُۥ لَقَوْلُ رَسُولٍ كَرِيمٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú (al-Ƙur’ān) ni ọ̀rọ̀ (tí A fi rán Jibrīl) Òjíṣẹ́, alápọ̀n-ọ́nlé,[1]

See all translations of this verse →

ذِى قُوَّةٍ عِندَ ذِى ٱلْعَرْشِ مَكِينٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelalágbára, ẹni pàtàkì ní ọ̀dọ̀ Ẹni t’Ó ni Ìtẹ́-ọlá,

See all translations of this verse →

مُّطَاعٍ ثَمَّ أَمِينٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaelẹni tí wọ́n ń tẹ̀lé àṣẹ rẹ̀ níbẹ̀ yẹn (nínú sánmọ̀), olùfọkàntán.

See all translations of this verse →

وَمَا صَاحِبُكُم بِمَجْنُونٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÀti pé ẹni yín (Ànábì Muhammad - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -) kì í ṣe wèrè.

See all translations of this verse →

وَلَقَدْ رَءَاهُ بِٱلْأُفُقِ ٱلْمُبِينِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÓ kúkú rí i nínú òfurufú kedere.[1]

See all translations of this verse →

وَمَا هُوَ عَلَى ٱلْغَيْبِ بِضَنِينٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÀti pé kì í ṣe ahun (tàbí ẹni-afurasí) lórí ìró ìkọ̀kọ̀ (tí A fi ránṣẹ́ sí i).

See all translations of this verse →

وَمَا هُوَ بِقَوْلِ شَيْطَٰنٍ رَّجِيمٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelAl-Ƙur’ān kì í sì ṣe ọ̀rọ̀ (tí A fi rán) aṣ-Ṣaetọ̄n, ẹni ẹ̀kọ̀.

See all translations of this verse →

فَأَيْنَ تَذْهَبُونَ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelNítorí náà, ibo l’ẹ̀ ń lọ?

See all translations of this verse →

إِنْ هُوَ إِلَّا ذِكْرٌ لِّلْعَٰلَمِينَ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelKí sì ni al-Ƙur’ān bí kò ṣe ìrántí fún gbogbo ẹ̀dá.

See all translations of this verse →

لِمَن شَآءَ مِنكُمْ أَن يَسْتَقِيمَ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(Ó wà) fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti dúró déédé.

See all translations of this verse →

وَمَا تَشَآءُونَ إِلَّآ أَن يَشَآءَ ٱللَّهُ رَبُّ ٱلْعَٰلَمِينَ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelẸ̀yin kò sì níí fẹ́ (láti dúró déédé) àyàfi tí Allāhu bá fẹ́, Olúwa gbogbo ẹ̀dá.

See all translations of this verse →

Looking for a topic? Try the meaning search — your question is scanned across all 6,236 verses.
Èdè — 70