caseriqÌwádìí ìtumọ̀ nínú Al-Ƙur'ān

Súrà Al-Balad البلد

20 verses · Mecca · revelation order 35

بِسْمِ ٱللَّهِ ٱلرَّحْمَٰنِ ٱلرَّحِيمِ لَآ أُقْسِمُ بِهَٰذَا ٱلْبَلَدِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÈmi (Allāhu) ń fi ìlú yìí[1] búra.

See all translations of this verse →

وَأَنتَ حِلٌّۢ بِهَٰذَا ٱلْبَلَدِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÌwọ sì ní ẹ̀tọ́ sí ìlú yìí (láti jagun nínú rẹ̀).[1]

See all translations of this verse →

وَوَالِدٍ وَمَا وَلَدَ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÈmi (Allāhu) ń fi òbí àti ohun tó bí búra.

See all translations of this verse →

لَقَدْ خَلَقْنَا ٱلْإِنسَٰنَ فِى كَبَدٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelDájúdájú A ṣẹ̀dá ènìyàn sínú ìṣòro.

See all translations of this verse →

أَيَحْسَبُ أَن لَّن يَقْدِرَ عَلَيْهِ أَحَدٌ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelṢé ó ń lérò pé ẹnì kan kò ní agbára lórí òun ni?

See all translations of this verse →

يَقُولُ أَهْلَكْتُ مَالًا لُّبَدًا

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÓ (sì) ń wí pé: “Èmi ti bàná dúkìá ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ (láti fi tako Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -)”

See all translations of this verse →

أَيَحْسَبُ أَن لَّمْ يَرَهُۥٓ أَحَدٌ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelṢé ó ń lérò pé ẹnì kan kò rí òun ni?

See all translations of this verse →

أَلَمْ نَجْعَل لَّهُۥ عَيْنَيْنِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelṢé A kò ṣe ojú méjì fún un?

See all translations of this verse →

وَلِسَانًا وَشَفَتَيْنِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÀti ahọ́n pẹ̀lú ètè méjì (tí A ṣe fún un)?

See all translations of this verse →

وَهَدَيْنَٰهُ ٱلنَّجْدَيْنِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelA sì fi ọ̀nà méjì mọ̀ ọ́n.

See all translations of this verse →

فَلَا ٱقْتَحَمَ ٱلْعَقَبَةَ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelKò sì lọ rin ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí níbi Iná!

See all translations of this verse →

وَمَآ أَدْرَىٰكَ مَا ٱلْعَقَبَةُ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelKí sì ni ó mú ọ mọ ohun tó ń jẹ́ ojú-ọ̀nà orí àpáta tó ṣòroó gùn fún ìgbàlà ẹ̀mí?

See all translations of this verse →

فَكُّ رَقَبَةٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(Òhun ni) títú ẹrú sílẹ̀ lóko ẹrú.

See all translations of this verse →

أَوْ إِطْعَٰمٌ فِى يَوْمٍ ذِى مَسْغَبَةٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelTàbí fífún ènìyàn ní oúnjẹ ní ọjọ́ ebi.

See all translations of this verse →

يَتِيمًا ذَا مَقْرَبَةٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikael(Ẹ lè fún) ọmọ-òrukàn nínú ẹbí,

See all translations of this verse →

أَوْ مِسْكِينًا ذَا مَتْرَبَةٍ

Yoruba Translation - Abu Rahimah Mikaeltàbí mẹ̀kúnnù tí kò ní gá tí kò ní go (olòṣì paraku).

See all translations of this verse →

ثُمَّ كَانَ مِنَ ٱلَّذِينَ ءَامَنُوا۟ وَتَوَاصَوْا۟ بِٱلصَّبْرِ وَتَوَاصَوْا۟ بِٱلْمَرْحَمَةِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelLẹ́yìn náà, kí ó wà nínú àwọn tó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n ń gbara wọn níyànjú sùúrù ṣíṣe, tí wọ́n sì tún ń gbara wọn níyànjú àánú ṣíṣe.

See all translations of this verse →

أُو۟لَٰٓئِكَ أَصْحَٰبُ ٱلْمَيْمَنَةِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÀwọn wọ̀nyẹn ni èrò ọwọ́ ọ̀tún.

See all translations of this verse →

وَٱلَّذِينَ كَفَرُوا۟ بِـَٔايَٰتِنَا هُمْ أَصْحَٰبُ ٱلْمَشْـَٔمَةِ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelÀwọn tó sì ṣàì gbàgbọ́ nínú àwọn āyah Wa, àwọn ni èrò ọwọ́ òsì.[1]

See all translations of this verse →

عَلَيْهِمْ نَارٌ مُّؤْصَدَةٌۢ

Yoruba Translation - Abu Rahimah MikaelWọ́n máa ti àwọn ìlẹ̀kùn Iná pa mọ́ wọn lórí pátápátá.

See all translations of this verse →

Looking for a topic? Try the meaning search — your question is scanned across all 6,236 verses.
Èdè — 70